Posts

Nigba ti Iṣejọba ba kuna: Idaamu Ọgbara Ikorodu ati aibikita Ijọba ipinlẹ Eko: Asiwaju kii sa. Wiwa ojutu si wahala niṣẹ aṣiwaju rere - GRV

Image
Ni ana, ajalu burúkú kan waye nilu Ikorodu latari  omi ọ̀gbàrá nla to ya kaakiri ile, to si ba dukia jẹ,  o tun fi ọpọlọpọ silẹ laini ibi aabo tabi ibùsùn.  Ajalu naa to yẹ ko gba   idahun pajawiri lẹsẹkẹsẹ lọwọ Ijọba Ipinle Eko, oṣenilanu osi tun jẹ ohun iyalẹnu nigba ti  kọmisọna ipinlẹ Eko fun eto ayika ati awọn orisun omi gba awọn olugbe agbegbe tọrọ naa kan lamọran pe ki wọn  kuro ni agbegbe naa. Idahun ti kọmisọna fii yii   kii ṣe ti ibanilọkan jẹ nikan, o tun ṣe afihan iru  iṣakoso ìjọba ipinlẹ Eko, iṣakoso to ni aibikita si iya ti awọn eyan doju kọ.  Eyi kii ṣe ajalu adayeba, o jẹ afihan kudiẹkudiẹ iṣejọba  labẹ ẹgbẹ oṣelu APC ti n dari ipinle Eko. Ibere to wa nilẹ bayii ni pe, ní gbati kọmisọna ni ki awọn eyan fi ile wọn silẹ, ibọ ni ki wọn lọ? Ṣé wọn pese afin ọba fun wọn ni, abi agbala awọn oloye abi ọgbà awọn ọlọpa ni wọn ni ki wọn ma lọ.  Ko sibi meji ti wọn yoo lọ ju oju popona lọ, wọn yoo wa ma w...

Sanwó-Olú ṣèfilọ́lẹ̀ iṣẹ́ àkànṣe níjọba ìbílẹ̀ onídàgbàsókè Bàrígà

Image
  Ọlaide Gold Iṣẹ akanṣe rọrun lati ṣe fawọn alaga ijọba ibilẹ kaakiri ipinlẹ Eko nitoripe wọn n gba ipin owo wọn pẹlu irọrun, Gomina Babajide Sanw o-Olu  lo sọrọ yii lasiko to  ṣi iṣẹ akanṣe nijọba ibilẹ Bariga. Yatọsi olu ileeṣẹ ijọba ibilẹ naa, gomina tun ṣi ojuna mọkanlelogun, ile ẹko alakọọbẹrẹ tuntun mẹta ati ojuko awọn oṣiṣe panapana, eyi ti Alaga ijọba ibilẹ onidagbasoke Bariga, Ọnarebu Kọlade Alabi, kọ fun igbayerọrun araalu. Gomina sanwo-olu sọ pe "Awọn iṣẹ akanṣe wọnyi jẹ ẹtọ araalu atipe ojuṣe ijọba ni ẹtọ lati ṣeto fun ilu,". Ó wa eọ alaga aṣẹṣẹyan iyen Arabinrin Bukọla Adedeji, lati ṣe aṣepari iṣẹ lori àwọn iṣẹ akanṣe yooku fun idagbasoke Bariga ati agbegbe rẹ wa lọ laisi ìmọ̀tara-ẹni-nìkan ki igba rẹ. Níbi ayẹyẹ ọjọọ naa, ni Alabi tun ti kede pe wọn ti ṣe ayipada orúkọ Community Road sí Babajide Sanwo-Olu Road gẹ́gẹ́ bí ibọwọ fun gomina fun atilẹyin rẹ.    Àwọn alẹnulọrọ ninu oṣelu ti wọn wa nibi eto naa ni, alaga ẹgbẹ APC nipinlẹ Eko,...

Sanwó-Olú tún fìdí òmìnira ìjọba ìbílẹ̀ múlẹ̀, lásìkò tó ṣí iṣẹ́ àkànṣe tí Ọ̀ṣínọ́wọ̀ kọ́ sí Àgbòyí-Kétu

Image
  Ọlaide Gold    Ẹṣẹ o gbero lọjọ Ẹti,Furaide to kọja,ṣeni ijọba ibilẹ onidagbasoke Agboyi-Ketu n rọ kẹkẹ, tawọn olugbe agbegbe naa si fidunnu wọn han bi Gomina Babajide Sanwo-Olu, ṣe ba wọn ṣiṣọ loju awọn iṣẹ akanṣe manigbagbe ti Ọnarebu Dele Ọṣinnọwọ ṣe. Alaga naa, lati fi ẹmi ifọmọniyanṣe to ni sawọn araalu han lo mu ko ṣe aṣepari iṣẹ lori awọn iṣẹ akanṣe manigbagbe bii, Ọtunba Bushura Alebiosu Multipurpose Building, ile ekọ alakọọbẹrẹ Agboyi Community, Agboyi Ketu ICT Hub, Papa iṣere Ọba Taiwo Adeṣẹgun Lamina ati awọn opopona mi-in, fun anfaani araalu.  Gomina Sanwo-Olu, ninu ọrọ ẹ ṣapejuwe awọn iṣẹ akanṣe naa gẹgẹ bi atọna idagbasoke agbegbe, o ni awọn iṣẹ ti  alaga naa ṣe wa ni ibamu pẹlu atẹ eto aato ilu ti iṣakoso oun gunle eyi ti  yoo jẹ ọkọ idagbasoke fawọn eeyan agbegbe naa.  Sanwo-Olu tun fasiko naa dupẹ lọwọ awọn eeyan agbegbe naa bi wọn ṣe fi ibo wọn sọrọ lati yan ẹni ti yoo tukọ ijọba ibilẹ naa bayii, Ọnarebu Adetọla Abubakar...

Revealed! Alhaja Queen Isimot Abake Abiola (Omo Opeki) : Leading The Elite Women Musicians Club of Nigeria To Unparalleled Success

Image
The Elite Women Musicians Club of Nigeria is experiencing unprecedented growth, and without any modicum of doubt, it can be attached to the capabilities of its esteemed President, Alhaja Queen Isimot Abake Abiola (Omo Opeki), PQ1ST. Under her charismatic leadership, the club has become a powerhouse of talent, innovation, and empowerment.   Her vision for the club extends beyond music, embracing a diverse membership of entertainers, businesswomen, and high-profile women who share her passion for promoting Nigeria’s rich cultural heritage. The President’s leadership has fostered a sense of unity and purpose among members, creating a platform for them to thrive and make a lasting impact.   With a strong foundation built on creativity, passion and cultural pride, the club is poised for continued growth and success, earning recognition and accolades for its commitment to empowering women and promoting Nigerian culture on the global stage. Her dedication and expertise ha...

Lẹ́yìn tó ṣí ojúnà Abáranjẹ̀:Sanwo-Olú ṣèlérí látí ṣe ojúna Ìṣẹri-Ọ̀ṣun,Ikọtun

Image
Ọlaide Gold   Awọn  olugbe agbegbe Abaranjẹ, Igando-Ikọtun nijọba ibilẹ Alimọṣọ ko le gbagbe Ọjọru Wẹside, ọjọ keji oṣu keje ọdun yii bọrọ bi gomina ipinlẹ Eko, Babajide Sanwo-Olu ati igbakeji rẹ, Dokita Ọbafẹmi Hamzat ṣe wa ṣi ojuna mọto ti wọn ṣẹṣẹ kọ pari ti wọn si kede pe o ti damulo. Sanwo-Olu bẹrẹ irinajo naa ni opopona Dọpẹmu tẹlẹ nijọba ibilẹ Agege ti wọn ti yi orukọ rẹ pada si opopona Babajide Sanwo-Olu bayii. Lẹyin naa lo darisi adugbo Abaranjẹ lagbegbe ijọba ibilẹ onidagbasoke Igando-Ikọtun labẹ agboorun ijoba ibilẹ Alimọṣọ. Nigba to n sọrọ níbi ayẹyẹ naa, Sanwo-Olu ni kii ṣe igba akọkọ ree toun wa ṣefilọlẹ iṣẹ akanṣẹ lagbegbe naa. O ni, ṣiṣe ojuna Abaranjẹ mu igbaye irọrun ba awọn olugbe adugbo kọọkan to yii ka nitoripe lilọ bibọ ọkọ ti jẹ irọrun bayii. Ni idahun si ẹbẹ awọn oriade lawọn agbegbe naa eyi ti wọn fi bẹbẹ fun afaara mọto nilu ikọtun, wọn ni nnkan to ma tun mu kí eto irinna rọrun lagbegbe naa siwaju si i niyẹn, ni gomina ba fun wọn lesi pe, ...

NNPP Chieftain, Ajadi, Tasks Politicians On Giving Back To The Society …..Receives ‘Father Abraham Distinguished Award’

Image
A Chieftain of the New Nigeria Peoples Party, (NNPP) in the South West, Ambassador Olufemi Ajadi Oguntoyinbo has charged politicians to always give back to the society either in form of job creation or empowerment for the people. Ajadi stated this, while speaking with journalists in Ibadan on Sunday after he received Father Abraham Distinguished Award as part of the 2025 Father’s Day Ceremony of the New Heritage Baptist Church Eniosa – Ibadan, Oyo State. Ambassador Ajadi was accompanied by a delegation of NNPP leaders, including the South-West Public Relations Officer, Hon. Kilamuwaye Badmus; Senatorial Candidate of the party in Ogun Central, Hon. Kehinde Teluwo; House of Assembly candidate of the party in Ifo Constituency 2, Hon. Akingbala Semiu; and House of Assembly 2023 candidate of the party in Ogun Waterside in 2023, Hon. Fatai Adenaya Modawoni. Others were the marketing representative of Bullion Records, Mr. Agboola Isaac Olakunle, and the Head of Media and Publicity Secretary o...

Ìjọba Èkó ṣèfilọ́lẹ̀ sítóòfù alálọpẹ́ tí kìí ṣèéfín ní Makòko

Ọkan lara agbegbe ti wọn kii saaba fojusi nipinlẹ Eko ni Makoko, ohun lo wa di ibudo ifilọlẹ sitoofu ti kii yọ eefin tijọba gbe kalẹ fun idile kọọkan lati ṣe afọmọ ayipada oju ọjọ. Igbesẹ yii wa ni ibamu pẹlu erongba ijọba lati pin adogan idana ti kii ṣeefin tiye rẹ jẹ ọgọrin miliọnu fawọn idile kọọkan kaakiri orileede Naijiria eyi ti wọn ṣafihan rẹ lawọn agbegbe to sun mọ eti omi. Ki imọtoto le tẹsiwaju lawọn agbegbe kọọkan atipe adogan igbalode naa yoo rọpo ṣiṣẹ amulo igi ti eefin rẹ le ṣakoba fun ilera. Ida mẹwaa lo maa kan ipinlẹ Eko, ninu sitoofu ti kii ṣeefin naa leyi to jasi pe, sitoofu miliọnu mẹjọ nijọba Eko fẹẹ pin fawọn eeyan agbegbe ijọba ibilẹ ati ijọba ibilẹ onidagbasoke mẹtadinlọgọta. Nigba to n sọrọ nibi ifilọlẹ naa lọjọru  Wẹside, ọṣẹ yii, Oludamọran Agba si  Gomina Babajide Sanwo-Olu lori ayipada oju ọjọ, Titilayọ Oshodi, tọka idi pataki ti Makoko ṣe jẹ afojusun ijọba tawọn si ma bẹrẹ pinpin ida akọkọ sitoofu naa ni ọgbọnjọ oṣu kẹfa, ọdun 2025. Gẹgẹ bi ọrọ rẹ...