Posts

Oluwaloni ṣedaro alaga kansu to ku lojiji l'Ekoo

Image
Inu ipayinkeke ati ibanujẹ ọkan ni gbogbo ara agbegbe Ayobo-Ipaja Local Council Development Area (LCDA) wa, latari iku alaga kẹta to jẹ ni agbegbe naa, Hon. Chief (Mrs.) Bolatito Shobowale.   Ẹni to jẹ adele alaga Ayobo-Ipaja LCDA, Otunba Ladi Oluwaloni (OLO 1), lọ sọrọ naa di mimọ, pẹlu ibanujẹ ọkan ni Oluwaloni fi kede iku oloogbe Shobowale ni ọjọ Ẹti ọsẹ yii.   O ni, iku arabinrin naa jẹ kayeefi fun awọn ati pe iṣẹlẹ to bani lọkan jẹ gidi ni iku naa jẹ,nitori oloogbe jẹ ẹni to da ni awujọ awọn.   Oluwaloni ṣe apejuwe Shobowale gẹgẹ bi eniyan rere to fẹ ilọsiwaju ilu, o ni oloogbe naa ki i ṣe olori nikan, o ni o jẹ alatilẹyin rere, igi lẹyin ọgba ọpọlọpọ awọn eeyan lo tun jẹ pẹlu.   Siwaju si i,  o ni oloogbe jẹ eni ti ki fifẹ ilu rẹ ṣere rara ti o si n ma fi gbogbo igba ja fun ijọba awarawa, ninu ọrọ rẹ, o sọ di mimọ pe gbogbo awọn tawọn wa ni Ipaja ni awọn yoo mọ ala iku rẹ nitori iṣẹ ti iya naa ṣe ninu aye awọn ara Ipaja ko kere rara.   Olu...

Sanwó-Olú ṣèlérí ètò ìrànlọ́wọ́ láti sàmì àyájọ́ àwọn obìnrin lágbàáyé

Image
Ọlaide Gold Ipa tawọn obinrin n ko ninu idagbasoke orileede ko kere, o to ki wọn ri iranlọwọ gba lọwọ ijọba lati le jẹ anfaani dẹmọnkiresi siwaju si i. Gomina ipinlẹ Eko, Babajide Sanwo-Olu lo sọrọ yii lọjọ Ẹti Furaide nibi ayẹyẹ ayajọ awọn obinrin lagbaaye eyi to waye ninu papa iṣere Onikan nilu Eko. Sanwo-Olu, fidi ẹ mulẹ pe,  ipa ti obinrin n ko ninu idagbasoke agbegbe wọn ati orileede lapapọ ko kere rara bakan naa lo ni igbesẹ lati ṣeranwọ fawọn obinrin naa wa ni ibamu pẹlu eto igbayerọrun ti ijọba Eko gunle. Oludanilẹkọọ ọjọ naa, to wa lati ẹka ẹkọ to n mojuto iṣedeede ọpọlọ ni fasiti imọ iṣegun ipinlẹ Eko,  Ọjọgbọn Olurotimi Coker ṣalaye pe, oriṣiriṣi iṣẹ ile tawọn obinrin ma n ṣe laarin wakati kan le ṣakoba fun iṣe deede ọpọlọ wọn, o ni, awọn obinrin o yẹ ki wọn tun ma gbe nnkan sọkan lẹyin lọta, fọṣọ,sebẹ ati itọju ọmọ. Olurotimi ni ṣeni ki wọn ma sọ ẹdun ọkan wọn jade ki ọkan le fuyẹ. O ni ki wọn maa ṣamulo awọn nnkan marun to ma n mu ki ọkan fuyẹ bii...

Ó ṣeéṣe kí ìpínlẹ́ Èkó má yáwó ṣiṣẹ́ àkànṣe-Ọpẹ́ George

Image
Ọlaide Gold Ipinlẹ Eko ko ni fi nnkan pamọ fawọn araalu idi niyẹn ti ẹka ileeṣe ijọba to n mojuto aato ilu ati eto iṣuna ṣe pe ipade pẹlu awọn oniroyin lọsẹ to kọja lati ṣalaye bi gomina ṣe fẹ nawo naa  atawọn nnkan tijọba fẹ nawo le lori.               Ninu ọrọ ikinni kaabọ sibi ipade naa to waye pẹlu awọn oniroyin ni Alausa n'Ikẹja ni kọmiṣanna iroyin, Ọgbẹni Gbenga Ọmọtọṣọ ti ṣalaye pe ipade naa dabi oriṣa teeyan n bọ lọdọọun ni toripe ni kete ti gomina ba ti gba  ibọwọlu owo iṣuna lo ma n pe iru ipade bẹẹ lati ṣalaye bi wọn ṣe fẹ nawo fawọn araalu kawọn eeyan le mọ nnkan tiwọn n fowo wọn ṣe.     Ọpẹ George, kọmiṣanna fun ọrọ aato ilu ati iṣuna ni ipinlẹ Eko ni iṣuna tiye rẹ ni tiriliọnu mẹta naira ni gomina gbe siwaju awọn aṣofin Eko tiwọn si ti bọwọlu u. O ni, afojusun ijọba ninu eto iṣuna naa ni lati ri dajupe awọn araalu jẹ anfaani ijọba awaarawa. Ọkunrin naa ni, kaakiri ẹkun idibo maraarun nipinlẹ Eko, iyẹn ...

Ẹ̀bùn òpin ọdún:Sanwó-Olú ṣèrànwọ́ fáwọ́n oníṣẹ́ ọwọ́ l'Ekoo

Image
Ọlaide Gold Gomina ipinlẹ Eko, Babajide Sanwo-Olu, ti sọpe oun ko ni yee ran araalu lọwọ nipa pipese awọn ohun amayedẹrun ati ṣiṣeranwọ fawọn ọmọ ẹkọṣẹ atawọn oniṣowo. O sọrọ naa lọjọru Wẹside, nibi ayẹyẹ ikẹkọọjade awọn oniṣẹ ọwọ tiwọn ṣetan labẹ ikẹkọọ ẹka ileeṣẹ to n ri sọrọ awọn awọn obinrin ati ironilgbara nipinlẹ Eko iyẹn Ministry of Women Affairs and Poverty Alleviation (WAPA) to waye ni Agidingbi, Ikeja. Ẹgbẹrun kan aabọ (1500) awọn tiwọn kọṣẹ yege naa niwọn gba ẹbun irinṣẹ ọfẹẹ bii maṣiini iranṣọ ati ẹyi to n lẹ okuta didan mọ aṣọ, ẹrọ ilọta, irinṣẹ yadirẹsa ati tawọn gẹrungẹrun, irinṣẹ awọn ketira, irinṣẹ wẹda ati eyi tiwọn fi nlẹ taili, iranlọwọ fawọn eleto ọgbin ati  bẹẹ bẹẹ lọ. Igbakeji gomina Eko, Dokita Ọbafẹmi Hamzat nigba to gbẹnu gomina Sanwo-Olu sọrọ nibi eto ikẹkọọjade naa sọpe ijọba n gbiyanju lati sọludẹrọ nipa ṣiṣeranwọ fawọn araalu. O ni itẹsiwaju ma deba ipinle naa bawọn araalu ba niṣẹ lọwọ. Idunnu ijọba Eko ni bawọn araalu paapaa julọ, awọn ọdọ...

Àtunṣe máa débá ìlànà ìkọ́lé l'Ékoo-Sanwó-Olú

Image
Ọlaide Gold Gomina ipinlẹ Eko, Babajide Sanwo-Olu ti fọkan awọn abanikọle balẹ pe wọn maa ni anfaani sawọn ohun amayedẹrun to le faaye gba awọn olokoowo ile lati ṣiṣẹ wọn nirọrun. Nibi ipatẹ idokoowo ilẹ ẹlẹẹkarun iyẹn Lagos Real Estate Marketplace Conference and Exhibitions, to waye  lọjọ Tuside ni gbọngan Eko Hotels ni Sanwo-Olu ti sọrọ naa bakan naa lo fi dawọn loju pe, abajade awọn alakalẹ ijọba maa rọju fun wọn lati ṣiṣẹ. Eto naa tiwọn pe akọri ẹ ni "Ṣiṣe atunṣe odiwọn ilẹ ati atunṣe iṣẹ abanikọle" ni gomina ti jẹ ko di mimọ pe, bawọn eeyan ṣe n kọle kaakiri tiwọn wọn o si bikita boya ori koto idaminu lawọn kọle si gbero bẹẹ ni ijọba Eko ti ṣetan lati ṣe atunṣe. Sanwo-Olu tẹsiwaju ninu ọrọ ẹ pe, iṣẹ abanikọle n fẹ amojuto toripe ẹni to n yọ  bukọọku ta ti sọrọ ẹ di abanikọle toripe o lowo lọwọ ṣugbọn ko bikita lati gbawọn akọṣẹmọṣẹ tiwọn nimọ nipa ile kikọ titi to fi pari iṣẹ. O lawọn iru ile bẹẹ kii tọjọ to fi maa dawo to si fi ẹmi awọn eeyan sinu ewu nitori...

Ìlera Èkó: àwọn elétò ìlèra sọ nípà ètò tuntun fáwọn aráàlú

Image
Ọlaide Gold    Erongba ijọba Eko ni lati ṣeto ilera pipe fawọn araalu atipe wọn ti n gbiyanju ko le jẹ itẹwọgba fun gbogbo eeyan fun igbayerọrun wọn. Akọwe Agba lẹka eto ilera Eko, Dokita Emmanuella Zamba lo sọrọ naa lonii ni ọfiisi ilera Eko n'Ikẹja lasiko ipade to waye pẹlu awọn oniroyin   Nibẹ lo ti ṣalaye pe, ẹka to n mojuto eto ilera Eko ti sa ipa wọn lati ri dajupe ilera pipe tẹ araalu lọwọ nitoripe bawọn eeyan ilu b n ṣojojo ko le si nnkan to n jẹ ilọsiwaju. Oriṣiiriṣii eto nijọba ipinlẹ Eko ti la kalẹ lẹka ilera tawọn eeyan si ti n jẹ anfaani rẹ tiwọn si  n dupẹ ṣugbọn iroyin naa  ko tii tan kalẹ to nitori naa lo ṣe ṣe pataki fawọn oniroyin lati tunbọ tan iroyin naa ka lori awọn atẹ iroyin wọn ko le fọnka sigboro ko si jẹ itẹwọgba paapaa julọ laarin awọn mẹkunnu. Abilekọ Tayọ Adetoro ṣalayé bi eto naa ṣe rọrun to lati ṣe fawọn mẹkunnu pẹlu owo pẹntọ. O mẹnuba bi ẹka ilera naa ṣe n gbawọn eeyan tiwọn n gbe nipinlẹ Ogun ṣugbọn tiwọn n ṣiṣẹ...

Gomina Sanwo-Olu fawọn akẹkọọ ileewe ẹkọṣẹ ọwọ lẹbun lasiko ayẹyẹ ikẹkọọjade wọn

Image
Gomina ipinlẹ Eko, Babajide Oluṣọla Sanwo-Olu nibi ayẹyẹ ikẹkọọjade awọn akẹkọọ gboye ileewe girama ẹkọṣẹ iyẹn Tẹkiniika ti ipinlẹ naa to waye ninu gbọngan "blueroof" lọgba ileeṣẹ tẹlifisan Eko lọjọ keji oṣu kejila niluu Ikẹja l'Ekoo lo fi ifarahan rẹ ṣe koriya fun wọn. Awọn akẹkọọ to le lẹgbẹrun meji ni wọn kọṣẹ yege, ti wọn si kẹkọọ gbọye l'awọn ile iwe sẹkọndiri Tẹkiniika mẹrẹẹrin to wa niluu Eko, nibẹ lawọn akẹkọọ kan si gbami ẹyẹ fifakọyọ ati pipegede ju awọn akẹgbẹ wọn yooku lọ. Awọn akẹkọọ to gbami ẹyẹ ẹni to peregede julọ ni, ẹni akọọkọ; Uchendu David lati ẹka ileewe ẹkọṣẹ ọwọ ti Ikọtun, ẹni keji, Daniel Salami, lati Agidingbi, ẹni kẹta, Benedict Wisdom, lati ẹka Ado-Soba, ẹni kẹrin, Adedeji Oluwapẹlumi J, Agidingbi, Boyejọ Joseph Babatunde, Ẹpẹ, Ọdọfin Moyọsọrẹ, Ikorodu, Arebisọla Grace, Ikọtun, Abalogu Mary Ifeoma, Ikọtun, Okpako Irughene Daniella, Ikọtun ati Ibiwọye Ẹniọla Modupẹ lati ileewe Tẹkiniika sẹkọndiri Agidingbi ni Ipinlẹ Eko. Ṣaaju kí ...