Tírélà sọ ìjánu rẹ̀ nù, ló bá já wọ inú agboolé lọ



Kayọde Ọmọtọṣọ

Niṣe lori ko ọpọlọpọ awọn eeyan yọ lọsan-an ọjọ Aiku, Sannde, ọsẹ yii nigba ti ọkọ tirela Dangote kan to ko simẹnti ṣadeede sọ ijanu rẹ nu to si ja wọ inu adugbo Isẹrin,to wa niluu Iṣẹyin,nipinlẹ Ọyọ, lọ.Akọroyin wa gbọ pe ohun ọkọ tirela yii sọ ijanu rẹ nu ni,lẹsẹkẹsẹ ti iṣẹlẹ ọhun ṣẹlẹ si ni awakọ tirela ọhun ati ẹni to tẹle e ti juba ehoro.

Awọn eeyan ni ẹru pe boya iṣẹlẹ yii mu ẹmi eeyan lọ lo fa a ti awakọ yii fi salọ.

Ẹnikan to ni ṣọọbu nibi tiṣẹlẹ ọhun ti ṣẹlẹ to pe orukọ ara rẹ ni Mama Dele ni pe Ọlọrun lo ni ki oun ti lọ si ṣọọṣi, bi bẹẹ kọ, tirela ọhun ko ba kan ka oun mọbẹ ti yoo si da ẹmi oun legbodo.

Comments

Popular posts from this blog

Àwọn ọmọ bíbí ìlú Òró bu ọlá fún ọba wọn tuntun

Wàhálà nlá nijọ sẹ̀lẹ́!Nítorí tùràrí wọ́n lu wòlíì lálùbami,làwọn aláṣẹ bá gbe ṣọ́ọ̀ṣì tìpa

Ojiṣẹ lṣẹdalẹ ṣatupalẹ ewi Wọle Ṣoyinka, 'Abiku' si ede Yoruba.