Iléeṣẹ́ mọ́tò GAC ṣàfihàn ọkọ̀ ẹgbẹ̀rún méjì nípínlẹ̀ Èkó

Gomina Babajide Sanwo-Olu ko le pa idunnu  rẹ mọra nigbati wọn mu kaakiri ọgba ileeṣẹ naa to si ri ohun ara awoyanu to n lọ nibẹ.

Sanwo-Olu gboṣuba kare fawọn alaṣẹ ileeṣẹ naa, O ni, ireti nla nigbesẹ naa jẹ toripe yoo pese iṣẹ rẹpẹtẹ fun awon eeyan ipinlẹ Eko ati Orileede Naijiria lapapọ. Ọkunrin akọkọ nipinlẹ naa ni, ileeṣẹ ti wọn ti to ọkọ ẹgbẹrun meji jọ naa yoo tunbọ mu ki ajọṣepọ to dan mọran wa  laarin awọn ileeṣẹ ile okeere ati Orileede Naijiria.

Ninu ọrọ Diana Chen, iyẹn alaga ileeṣẹ naa, O ni, lọdun 2020 ni pọpọṣinṣin idasilẹ ileeṣẹ naa bẹrẹ lasiko isede atankalẹ arun Korona, o ni, asiko naa ni ibaṣepọ waye laarin ileeṣẹ naa pẹlu ijọba ipinlẹ Eko, nigba naa ni wọn tọwọ bọ iwe adehun lati da ileeṣẹ naa silẹ.



Comments

Popular posts from this blog

Àwọn ọmọ bíbí ìlú Òró bu ọlá fún ọba wọn tuntun

Wàhálà nlá nijọ sẹ̀lẹ́!Nítorí tùràrí wọ́n lu wòlíì lálùbami,làwọn aláṣẹ bá gbe ṣọ́ọ̀ṣì tìpa

Ojiṣẹ lṣẹdalẹ ṣatupalẹ ewi Wọle Ṣoyinka, 'Abiku' si ede Yoruba.